< Psalms 137 >
1 Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.
Sur les bords des fleuves de Babylone, nous nous sommes assis. Oui, nous avons pleuré, quand nous nous sommes souvenus de Sion.
2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò, tí ó wà láàrín rẹ̀.
Sur les saules de ce pays, nous avons raccroché nos harpes.
3 Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa, àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá; wọn wí pé, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!”
Car là, ceux qui nous ont emmenés en captivité nous ont demandé des chants. Ceux qui nous tourmentaient exigeaient des chants de joie: « Chantez-nous une des chansons de Sion! »
4 Àwa ó ti ṣe kọ orin Olúwa ní ilẹ̀ àjèjì
Comment pouvons-nous chanter le chant de Yahvé dans un pays étranger?
5 Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.
Si je t'oublie, Jérusalem, que ma main droite oublie son habileté.
6 Bí èmi kò bá rántí rẹ, jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi; bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú olórí ayọ̀ mi gbogbo.
Que ma langue se colle au palais si je ne me souviens pas de toi, si je ne préfère pas Jérusalem à ma principale joie.
7 Olúwa rántí ọjọ́ Jerusalẹmu, lára àwọn ọmọ Edomu, àwọn ẹni tí ń wí pé, “Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!”
Souviens-toi, Yahvé, des enfants d'Édom, au jour de Jérusalem, qui a dit: « Rasez-la! Rasez-le jusqu'à ses fondations! »
8 Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun; ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ bí ìwọ ti rò sí wa.
Fille de Babylone, vouée à la destruction, celui qui vous rembourse sera heureux, comme vous l'avez fait pour nous.
9 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.
Il sera heureux, qui prend et écrase vos petits contre le rocher.