< Psalms 137 >

1 Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.
On the floodis of Babiloyne there we saten, and wepten; while we bithouyten on Syon.
2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò, tí ó wà láàrín rẹ̀.
In salewis in the myddil therof; we hangiden vp oure orguns.
3 Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa, àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá; wọn wí pé, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!”
For thei that ledden vs prisoners; axiden vs there the wordis of songis. And thei that ledden awei vs seiden; Synge ye to vs an ympne of the songis of Syon.
4 Àwa ó ti ṣe kọ orin Olúwa ní ilẹ̀ àjèjì
Hou schulen we singe a songe of the Lord; in an alien lond?
5 Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.
If Y foryete thee, Jerusalem; my riyt hond be youun to foryeting.
6 Bí èmi kò bá rántí rẹ, jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi; bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú olórí ayọ̀ mi gbogbo.
Mi tunge cleue to my chekis; if Y bithenke not on thee. If Y purposide not of thee, Jerusalem; in the bigynnyng of my gladnesse.
7 Olúwa rántí ọjọ́ Jerusalẹmu, lára àwọn ọmọ Edomu, àwọn ẹni tí ń wí pé, “Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!”
Lord, haue thou mynde on the sones of Edom; for the dai of Jerusalem. Whiche seien, Anyntische ye, anyntische ye; `til to the foundement ther ynne.
8 Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun; ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ bí ìwọ ti rò sí wa.
Thou wretchid douyter of Babiloyne; he is blessid, that `schal yelde to thee thi yelding, which thou yeldidist to vs.
9 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.
He is blessid, that schal holde; and hurtle doun hise litle children at a stoon.

< Psalms 137 >