< Psalms 137 >

1 Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.
By the waters of Babylon there we sat, and we wept at the thought of Zion.
2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò, tí ó wà láàrín rẹ̀.
There on the poplars we hung our harps.
3 Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa, àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá; wọn wí pé, “Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!”
For there our captors called for a song: our tormentors, rejoicing, saying: “Sing us one of the songs of Zion.”
4 Àwa ó ti ṣe kọ orin Olúwa ní ilẹ̀ àjèjì
How can we sing the Lord’s song in the foreigner’s land?
5 Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.
If I forget you, Jerusalem, may my right hand wither.
6 Bí èmi kò bá rántí rẹ, jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi; bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú olórí ayọ̀ mi gbogbo.
May my tongue stick to the roof of my mouth, if I am unmindful of you, or don’t set Jerusalem above my chief joy.
7 Olúwa rántí ọjọ́ Jerusalẹmu, lára àwọn ọmọ Edomu, àwọn ẹni tí ń wí pé, “Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!”
Remember the Edomites, Lord, the day of Jerusalem’s fall, when they said, “Lay her bare, lay her bare, right down to her very foundation.”
8 Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun; ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ bí ìwọ ti rò sí wa.
Babylon, despoiler, happy are those who pay you back for all you have done to us.
9 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.
Happy are they who seize and dash your children against the rocks.

< Psalms 137 >