< Psalms 136 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
Give thanks to Yahweh, for he is good, for his loving kindness endures forever.
2 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
Give thanks to the God of gods, for his loving kindness endures forever.
3 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
Give thanks to the Lord of lords, for his loving kindness endures forever;
4 Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
to him who alone does great wonders, for his loving kindness endures forever;
5 Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
to him who by understanding made the heavens, for his loving kindness endures forever;
6 Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
to him who spread out the earth above the waters, for his loving kindness endures forever;
7 Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
to him who made the great lights, for his loving kindness endures forever;
8 Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
the sun to rule by day, for his loving kindness endures forever;
9 Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
the moon and stars to rule by night, for his loving kindness endures forever;
10 Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
to him who struck down the Egyptian firstborn, for his loving kindness endures forever;
11 Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
and brought out Israel from among them, for his loving kindness endures forever;
12 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
with a strong hand, and with an outstretched arm, for his loving kindness endures forever;
13 Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
to him who divided the Red Sea apart, for his loving kindness endures forever;
14 Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
and made Israel to pass through the middle of it, for his loving kindness endures forever;
15 Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
but overthrew Pharaoh and his army in the Red Sea, for his loving kindness endures forever;
16 Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
to him who led his people through the wilderness, for his loving kindness endures forever;
17 Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
to him who struck great kings, for his loving kindness endures forever;
18 Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
and killed mighty kings, for his loving kindness endures forever;
19 Sihoni, ọba àwọn ará Amori
Sihon king of the Amorites, for his loving kindness endures forever;
Og king of Bashan, for his loving kindness endures forever;
21 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
and gave their land as an inheritance, for his loving kindness endures forever;
22 Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
even a heritage to Israel his servant, for his loving kindness endures forever;
23 Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
who remembered us in our low estate, for his loving kindness endures forever;
24 Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
and has delivered us from our adversaries, for his loving kindness endures forever;
25 Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
who gives food to every creature, for his loving kindness endures forever.
26 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;
Oh give thanks to the God of heaven, for his loving kindness endures forever.