< Psalms 136 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun;
O give thanks unto Yhwh; for he is good: for his mercy endureth for ever.
2 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run àwọn ọlọ́run:
O give thanks unto the God of gods: for his mercy endureth for ever.
3 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa àwọn olúwa,
O give thanks to the Lord of lords: for his mercy endureth for ever.
4 Fún Òun nìkan tí ń ṣiṣẹ́ ìyanu ńlá;
To him who alone doeth great wonders: for his mercy endureth for ever.
5 Fún ẹni tí ó fi ọgbọ́n dá ọ̀run;
To him that by wisdom made the heavens: for his mercy endureth for ever.
6 Fún ẹni tí ó tẹ́ ilẹ̀ lórí omi;
To him that stretched out the earth above the waters: for his mercy endureth for ever.
7 Fún ẹni tí ó dá àwọn ìmọ́lẹ̀ ńlá;
To him that made great lights: for his mercy endureth for ever:
8 Òòrùn láti jẹ ọba ọ̀sán;
The sun to rule by day: for his mercy endureth for ever:
9 Òṣùpá àti ìràwọ̀ láti jẹ ọba òru;
The moon and stars to rule by night: for his mercy endureth for ever.
10 Fún ẹni tí ó kọlu Ejibiti lára àwọn àkọ́bí wọn;
To him that smote Egypt in their firstborn: for his mercy endureth for ever:
11 Ó sì mú Israẹli jáde kúrò láàrín wọn;
And brought out Israel from among them: for his mercy endureth for ever:
12 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà;
With a strong hand, and with a stretched out arm: for his mercy endureth for ever.
13 Fún ẹni tí ó pín Òkun pupa ní ìyà;
To him which divided the Red sea into parts: for his mercy endureth for ever:
14 Ó sì mú Israẹli kọjá láàrín rẹ̀
And made Israel to pass through the midst of it: for his mercy endureth for ever:
15 Ṣùgbọ́n ó bi Farao àti ogun rẹ̀ ṣubú nínú Òkun pupa;
But overthrew Pharaoh and his army in the Red sea: for his mercy endureth for ever.
16 Fún ẹni tí ó sin àwọn ènìyàn rẹ̀ la aginjù já
To him which led his people through the wilderness: for his mercy endureth for ever.
17 Fún ẹni tí ó kọlu àwọn ọba ńlá;
To him which smote great kings: for his mercy endureth for ever:
18 Ó sì pa àwọn ọba olókìkí
And slew famous kings: for his mercy endureth for ever:
19 Sihoni, ọba àwọn ará Amori
Sihon king of the Amorites: for his mercy endureth for ever:
20 Àti Ogu, ọba Baṣani;
And Og the king of Bashan: for his mercy endureth for ever:
21 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní,
And gave their land for an heritage: for his mercy endureth for ever:
22 Ìní fún Israẹli, ìránṣẹ́ rẹ̀,
Even an heritage unto Israel his servant: for his mercy endureth for ever.
23 Ẹni tí ó rántí wa ní ìwà ìrẹ̀lẹ̀ wa;
Who remembered us in our low estate: for his mercy endureth for ever:
24 Ó sì dá wa ní ìdè lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa;
And hath redeemed us from our enemies: for his mercy endureth for ever.
25 Ẹni tí ó fi oúnjẹ fún àwọn ẹ̀dá gbogbo
Who giveth food to all flesh: for his mercy endureth for ever.
26 Ẹ fi ọpẹ́ fún Ọlọ́run ọ̀run;
O give thanks unto the God of heaven: for his mercy endureth for ever.

< Psalms 136 >