< Psalms 135 >

1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Alleluja. Chwalcie imię PANA; chwalcie, słudzy PANA;
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
Którzy stoicie w domu PANA, w przedsionkach domu naszego Boga.
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Chwalcie PANA, bo PAN jest dobry; śpiewajcie jego imieniu, bo [jest] wdzięczne.
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
PAN bowiem wybrał sobie Jakuba i Izraela na swoją szczególną własność.
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Wiem, że wielki jest PAN, a nasz Pan jest ponad wszystkimi bogami.
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
Wszystko, co PAN chce, to czyni na niebie i na ziemi, w morzu i we wszystkich głębinach.
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
On sprawia, że mgły wznoszą się z krańców ziemi; wywołuje błyskawice i deszcz, wydobywa wiatr ze swoich skarbców;
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
Poraził pierworodnych w Egipcie, od człowieka aż do zwierzęcia.
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
Zesłał znaki i cuda pośród ciebie, Egipcie; na faraona i na wszystkie jego sługi.
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
Pobił wiele narodów i zgładził potężnych królów;
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
Sychona, króla Amorytów, i Oga, króla Baszanu, i wszystkie królestwa Kanaanu;
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
I dał ich ziemię w dziedzictwo, w dziedzictwo Izraelowi, swemu ludowi.
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
Twoje imię, PANIE, [trwa] na wieki; twoja pamięć, PANIE, z pokolenia na pokolenie.
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Bo PAN będzie sądzić swój lud i zmiłuje się nad swymi sługami.
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Bożki pogan to srebro i złoto, dzieło ludzkich rąk.
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Mają usta, ale nie mówią; mają oczy, ale nie widzą;
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
Mają uszy, ale nie słyszą, i nie ma oddechu w ich ustach.
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Podobni są do nich ci, którzy je robią, i wszyscy, którzy w nich pokładają ufność.
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
Domu Izraela, błogosławcie PANA; domu Aarona, błogosławcie PANA.
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
Domu Lewiego, błogosławcie PANA; wy, którzy się boicie PANA, błogosławcie PANA.
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Niech będzie błogosławiony z Syjonu PAN, który mieszka w Jeruzalem. Alleluja.

< Psalms 135 >