< Psalms 135 >

1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Halleluja. Chwalcie imię Pańskie, chwalcie słudzy Pańscy.
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
Którzy stawacie w domu Pańskim, w sieniach domu Boga naszego.
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Chwalcież Pana, albowiem to Pan dobry; śpiewajcież imieniowi jego, boć jest wdzięczne.
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
Albowiem sobie Jakóba Pan obrał, i Izraela za własność swoję.
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Jać zaiste uznaję, iż wielki jest Pan, a Pan nasz jest nad wszystkich bogów.
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
Wszystko co chce Pan, to czyni, na niebie i na ziemi, w morzu i we wszystkich przepaściach.
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
Który czyni, że występują pary od kończyn ziemi; błyskawice i dżdże przywodzi, wywodzi wiatr z skarbów swoich;
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
Który pobił pierworodztwa w Egipcie, od człowieka aż do bydlęcia.
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
Posłał znaki i cuda w pośród ciebie, Egipcie! na Faraona i na wszystkich sług jego.
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
Który poraził wiele narodów, a pobił królów możnych;
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
Sehona, króla Amorejskiego, i Oga, króla Basańskiego, i wszystkie królestwa Chananejskie.
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
I dał ziemię ich w dziedzictwo, w dziedzictwo Izraelowi, ludowi swemu.
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
Panie! imię twoje na wieki; Panie! pamiątka twoja od narodu do narodu.
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Zaite Pan sądzić będzie lud swój, a nad sługami swymi zmiłuje się.
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Ale bałwany pogańskie, srebro i złoto, są robotą rąk ludzkich.
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Usta mają, a nie mówią, oczy mają, a nie widzą;
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
Uszy mają, a nie słyszą, ani mają tchnienia w ustach swoich.
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Niech im podobni będą, którzy je robią, i wszyscy, którzy w nich ufają.
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
Domie Izraelski! błogosławcie Panu; domie Aaronowy! błogosławcie Panu.
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
Domie Lewiego! błogosławcie Panu, którzy się boicie Pana, błogosławcie Panu.
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Błogosławiony Pan z Syonu, który mieszka w Jeruzalemie. Halleluja.

< Psalms 135 >