< Psalms 135 >

1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
هللویاه، نام خداوند را تسبیح بخوانید! ای بندگان خداوند تسبیح بخوانید!۱
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
‌ای شما که در خانه خداوندمی ایستید، در صحن های خانه خدای ما.۲
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
هللویاه، زیرا خداوند نیکو است! نام او رابسرایید زیرا که دلپسند است.۳
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
زیرا که خداوندیعقوب را برای خود برگزید، و اسرائیل را به جهت ملک خاص خویش.۴
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
زیرا می‌دانم که خداوند بزرگ است و خداوند ما برتر است ازجمیع خدایان.۵
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
هر‌آنچه خداوند خواست آن را کرد، درآسمان و در زمین و در دریا و در همه لجه‌ها.۶
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
ابرها را از اقصای زمین برمی آورد و برقها رابرای باران می‌سازد و بادها را از مخزنهای خویش بیرون می‌آورد.۷
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
که نخست زادگان مصررا کشت، هم از انسان هم از بهایم.۸
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
آیات ومعجزات را در وسط تو‌ای مصر فرستاد، برفرعون و بر جمیع بندگان وی.۹
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
که امتهای بسیاررا زد و پادشاهان عظیم را کشت.۱۰
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
سیحون پادشاه اموریان و عوج پادشاه باشان و جمیع ممالک کنعان را.۱۱
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
و زمین ایشان را به میراث داد، یعنی به میراث قوم خود اسرائیل.۱۲
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
‌ای خداوند، نام توست تا ابدالاباد؛ و‌ای خداوند، یادگاری توست تا جمیع طبقات.۱۳
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
زیرا خداوند قوم خود را داوری خواهد نمودو بر بندگان خویش شفقت خواهد فرمود.۱۴
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
بتهای امتها طلا و نقره می‌باشند، عمل دستهای انسان.۱۵
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
دهنها دارند و سخن نمی گویند؛ چشمان دارند و نمی بینند؛۱۶
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
گوشهادارند و نمی شنوند بلکه در دهان ایشان هیچ نفس نیست.۱۷
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
سازندگان آنها مثل آنها می‌باشند وهرکه بر آنها توکل دارد.۱۸
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
‌ای خاندان اسرائیل، خداوند را متبارک خوانید. ای خاندان هارون، خداوند را متبارک خوانید.۱۹
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
‌ای خاندان لاوی، خداوند را متبارک خوانید. ای ترسندگان خداوند، خداوند را متبارک خوانید.۲۰
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
خداونداز صهیون متبارک باد، که در اورشلیم ساکن است. هللویاه.۲۱

< Psalms 135 >