< Psalms 135 >
1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Louez l'Éternel! Louez le nom de l'Éternel; Louez-le, serviteurs de l'Éternel,
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
Qui vous tenez dans la maison de l'Éternel, Dans les parvis de la maison de notre Dieu!
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Louez l'Éternel; car l'Éternel est bon! Psalmodiez à la gloire de son nom; car il est clément:
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
L'Éternel a choisi pour lui Jacob; Il a pris Israël pour son partage.
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Oui, je sais que l'Éternel est grand, Et que notre Seigneur est au-dessus de tous les dieux.
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
L'Éternel fait tout ce qui lui plaît, Dans les cieux et sur la terre. Dans les mers et dans tous les abîmes.
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
Il fait monter des extrémités de la terre les nuées; Il fait briller les éclairs au milieu même de la pluie; Il fait sortir le vent de ses réservoirs.
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
C'est lui qui a frappé les premiers-nés de l'Egypte, Depuis les hommes jusqu'aux bêtes.
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
Il a fait paraître au milieu de toi, ô Egypte, Des signes et des prodiges, Pour châtier Pharaon et tous ses serviteurs.
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
Il a frappé de grandes nations. Et mis à mort de puissants rois:
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
Sihon, roi des Amoréens. Og, roi de Basan, Et tous les rois de Canaan.
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
Il a fait de leur territoire le patrimoine, Oui, le patrimoine d'Israël, son peuple.
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
Éternel, ton nom demeure à perpétuité; Éternel, ta mémoire dure d'âge en âge!
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
L'Éternel fera droit à son peuple. Et il aura compassion de ses serviteurs.
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Les idoles des nations ne sont que de l'argent et de l'or. Oeuvres des mains de l'homme,
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Elles ont une bouche, et elles ne parlent pas; Elles ont des yeux, et elles ne voient pas;
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
Elles ont des oreilles, et elles n'entendent pas, Et il n'y a point de souffle dans leur bouche.
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Ceux qui les fabriquent, Et tous ceux qui mettent leur confiance en elles, Leur deviendront semblables!
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
Maison d'Israël, bénis l'Éternel! Maison d'Aaron, bénis l'Éternel!
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
Maison de Lévi, bénis l'Éternel! Vous qui craignez l'Éternel, bénissez l'Éternel!
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Béni soit, de Sion, l'Éternel Qui fait de Jérusalem sa demeure! Louez l'Éternel!