< Psalms 135 >

1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Lover Herrens Navn, lover, I Herrens Tjenere!
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
I, som staa i Herrens Hus, i vor Guds Hus's Forgaarde.
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Lover Herren; thi Herren er god; lovsynger hans Navn; thi det er lifligt.
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
Thi Herren har udvalgt sig Jakob, Israel til sin Ejendom.
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Thi jeg ved, at Herren er stor, og at vor Herre er større end alle Guder.
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
Herren gør alt, hvad ham behager, i Himmelen og paa Jorden, i Havene og i alle Afgrunde.
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
Han gør, at Dampe opstige fra Jordens Grænse; han gør Lynene til Regn, han udfører Vejret af sine Forraadskamre.
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
Han, som slog de førstefødte i Ægypten, baade Mennesker og Dyr;
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
han sendte Tegn og underlige Ting i din Midte, Ægypten! paa Farao og paa alle hans Tjenere;
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
han, som slog mange Folk og ihjelslog stærke Konger:
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
Amoriternes Konge Sihon og Basans Konge Og samt alle Riger i Kanaan;
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
og han gav deres Land til Arv, til Arv for sit Folk Israel.
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
Herre! dit Navn bliver evindelig; Herre! din Ihukommelse bliver fra Slægt til Slægt.
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Thi Herren skal dømme sit Folk, og det skal angre ham for hans Tjeneres Skyld.
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Hedningernes Afguder ere Sølv og Guld, et Menneskes Hænders Gerning.
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
De have Mund, men tale ikke; de have Øjne, men se ikke.
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
De have Øren, men høre ikke, og der er ingen Aande i deres Mund.
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Ligesom disse ere, saa blive de, som gøre dem, ja, hver den, som forlader sig paa dem.
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
Israels Hus! lover Herren; Arons Hus! lover Herren.
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
Levis Hus! lover Herren; I, som frygte Herren! lover Herren.
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Lovet være Herren fra Zion, han, som bor i Jerusalem! Halleluja!

< Psalms 135 >