< Psalms 135 >

1 Ẹ yin Olúwa. Ẹ yin orúkọ Olúwa; ẹ yìn ín, ẹ̀yin ìránṣẹ́ Olúwa.
Halelujah. Chvalte jméno Hospodinovo, chvalte služebníci Hospodinovi,
2 Ẹ̀yin tí ń dúró ní ilé Olúwa, nínú àgbàlá ilé Ọlọ́run wa.
Kteříž stáváte v domě Hospodinově, v síňcích domu Boha našeho.
3 Ẹ yin Olúwa: nítorí tí Olúwa ṣeun; ẹ kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ̀; nítorí tí ó dùn.
Chvalte Hospodina, nebo jest dobrý Hospodin; žalmy zpívejte jménu jeho, nebo rozkošné jest.
4 Nítorí tí Olúwa ti yan Jakọbu fún ara rẹ̀; àní Israẹli fún ìṣúra ààyò rẹ̀.
Jákoba zajisté sobě vyvolil Hospodin, a Izraele za svůj lid zvláštní.
5 Nítorí tí èmi mọ̀ pé Olúwa tóbi, àti pé Olúwa jù gbogbo òrìṣà lọ.
Jáť jsem jistě seznal, že veliký jest Hospodin, a Pán náš nade všecky bohy.
6 Olúwa ṣe ohunkóhun tí ó wù ú, ní ọ̀run àti ní ayé, ní Òkun àti ní ọ̀gbun gbogbo.
Cožkoli chce Hospodin, to činí na nebi i na zemi, v moři i ve všech propastech.
7 Ó mú ìkùùkuu gòkè láti òpin ilẹ̀ wá: ó dá mọ̀nàmọ́ná fún òjò: ó ń mú afẹ́fẹ́ ti inú ilẹ̀ ìṣúra rẹ̀ wá.
Kterýž způsobuje to, že páry vystupují od krajů země; blýskání s deštěm přivodí, a vyvodí vítr z pokladů svých.
8 Ẹni tí ó kọlu àwọn àkọ́bí Ejibiti, àti ti ènìyàn àti ti ẹranko.
Kterýž zbil prvorozené v Egyptě, od člověka až do hovada.
9 Ẹni tí ó rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí àárín rẹ̀, ìwọ Ejibiti, sí ara Farao àti sí ara àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ gbogbo.
Poslal znamení a zázraky u prostřed tebe, Egypte, na Faraona i na všecky služebníky jeho.
10 Ẹni tí ó kọlu àwọn orílẹ̀-èdè púpọ̀, tí ó sì pa àwọn alágbára ọba.
Kterýž pobil národy mnohé, a zbil krále mocné,
11 Sihoni, ọba àwọn ará Amori, àti Ogu, ọba Baṣani, àti gbogbo ìjọba Kenaani:
Seona krále Amorejského, a Oga krále Bázan, i všecka království Kananejská.
12 Ó sì fi ilẹ̀ wọn fún ni ní ìní, ìní fún Israẹli, ènìyàn rẹ̀.
A dal zemi jejich v dědictví, v dědictví Izraelovi lidu svému.
13 Olúwa orúkọ rẹ dúró láéláé; ìrántí rẹ Olúwa, láti ìrandíran.
Hospodine, jméno tvé na věky, Hospodine, památka tvá od národu až do pronárodu.
14 Nítorí tí Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀, yóò sì ṣe ìyọ́nú sí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Souditi zajisté bude Hospodin lid svůj, a služebníkům svým bude milostiv.
15 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Ale modly pohanské stříbro a zlato, dílo rukou lidských,
16 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀; wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Ústa mají a nemluví, oči mají a nevidí.
17 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀; bẹ́ẹ̀ ni kò si èémí kan ní ẹnu wọn.
Uši mají a neslyší, nýbrž ani ducha není v ústech jejich.
18 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn: gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Buďtež jim podobní, kteříž je dělají, a kdožkoli naději svou v nich skládají.
19 Ẹ̀yin ara ilé Israẹli, ẹ fi ìbùkún fún Olúwa, ẹ̀yin ará ilé Aaroni, fi ìbùkún fún Olúwa.
Dome Izraelský, dobrořečte Hospodinu; dome Aronův, dobrořečte Hospodinu.
20 Ẹ̀yin ará ilé Lefi, fi ìbùkún fún Olúwa; ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, fi ìbùkún fún Olúwa.
Dome Léví, dobrořečte Hospodinu; kteříž se bojíte Hospodina, dobrořečte Hospodinu.
21 Olùbùkún ni Olúwa, láti Sioni wá, tí ń gbé Jerusalẹmu. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Požehnaný Hospodin z Siona, kterýž přebývá v Jeruzalémě. Halelujah.

< Psalms 135 >