< Psalms 132 >
1 Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
En vallfartssång. Tänk, HERRE, David till godo, på allt vad han fick lida,
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
han som svor HERREN en ed och gjorde ett löfte åt den Starke i Jakob;
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
"Jag skall icke gå in i den hydda där jag bor, ej heller bestiga mitt viloläger,
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
jag skall icke unna mina ögon sömn eller mina ögonlock slummer,
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
förrän jag har funnit en plats åt HERREN, en boning åt den Starke i Jakob."
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
Ja, vi hörde därom i Efrata, vi förnummo det i skogsbygden.
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
Låtom oss gå in i hans boning, tillbedja vid hans fotapall.
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
Stå upp, HERRE, och kom till din vilostad, du och din makts ark.
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
Dina präster vare klädda i rättfärdighet, och dina fromma juble.
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
För din tjänare Davids skull må du icke visa tillbaka din smorde.
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
HERREN har svurit David en osviklig ed, som han icke skall rygga: "Av ditt livs frukt skall jag sätta konungar på din tron.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
Om dina barn hålla mitt förbund och hålla mitt vittnesbörd, som jag skall lära dem, så skola ock deras barn till evig tid få sitta på din tron.
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
Ty HERREN har utvalt Sion, där vill han hava sin boning.
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
Detta är min vilostad till evig tid; här skall jag bo, ty till detta ställe har jag lust.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
Dess förråd skall jag rikligen välsigna, åt dess fattiga skall jag giva bröd till fyllest.
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
Dess präster skall jag kläda i frälsning, och dess fromma skola jubla högt.
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
Där skall jag låta ett horn skjuta upp åt David; där har jag rett till en lampa åt min smorde.
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
Hans fiender skall jag kläda i skam, men på honom skall hans krona glänsa."