< Psalms 132 >

1 Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Um Canto de Ascensões. Yahweh, lembre-se de David e de toda sua aflição,
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
como ele jurou a Javé, e fez um voto ao Poderoso de Jacob:
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
“Certamente eu não entrarei na estrutura de minha casa, nem subir na minha cama;
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
Não vou dar sono a meus olhos, ou dormir até minhas pálpebras,
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
até encontrar um lugar para Yahweh, uma moradia para o Poderoso de Jacob”.
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
Veja, ouvimos falar disso em Ephrathah. Encontramo-lo no campo de Jaar.
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
“Entraremos em sua morada. Nós adoraremos a seus pés”.
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
Levante-se, Yahweh, em seu lugar de descanso, você, e a arca de suas forças.
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
Let seus padres sejam vestidos com retidão. Deixem seus santos gritar de alegria!
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
Para o bem de seu servo David, não vire o rosto de seu ungido.
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
Yahweh jurou a David em verdade. Ele não se virará a partir disso: “Colocarei o fruto de seu corpo em seu trono”.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
Se seus filhos mantiverem meu pacto, meu testemunho que lhes ensinarei, seus filhos também se sentarão em seu trono para sempre mais”.
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
Para Yahweh escolheu Zion. Ele o desejou para sua moradia.
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
“Este é meu lugar de descanso para sempre. Vou viver aqui, pois o desejei.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
Abençoarei abundantemente sua provisão. Vou satisfazer seus pobres com pão.
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
I também vestirá seus padres com a salvação. Seus santos gritarão em voz alta de alegria.
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
Vou fazer o chifre de David brotar ali. Ordenei uma lâmpada para meu ungido.
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
Vestirei seus inimigos de vergonha, mas sobre si mesmo, sua coroa vai brilhar”.

< Psalms 132 >