< Psalms 132 >

1 Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
سرود زائران به هنگام بالا رفتن به اورشلیم. ای خداوند، داوود و تمام سختیهای او را به یاد آور
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
که چگونه برای خداوند قسم خورد و برای قدیرِ یعقوب نذر کرده، گفت:
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
«به خانۀ خود نخواهم رفت؛ و در بستر خویش آرام نخواهم گرفت،
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
خواب به چشمانم راه نخواهم داد، و نه سنگینی به مژگانم،
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
تا وقتی که مکانی برای ساختن خانه‌ای برای خداوندم بیابم و مسکنی برای قدیرِ یعقوب.»
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
در بیت‌لحم راجع به صندوق عهد تو شنیدیم، و در صحرای یعاریم آن را یافتیم.
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
گفتیم: «بیایید به مسکن خداوند وارد شویم، و در پیشگاه او پرستش کنیم.»
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
ای خداوند، برخیز و همراه صندوق عهد خود که نشانهٔ قدرت توست به عبادتگاه خود بیا!
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
باشد که کاهنان تو جامهٔ پاکی و راستی را در بر کنند و قوم تو با شادی سرود خوانند!
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
ای خداوند، به خاطر بنده‌ات داوود، پادشاه برگزیده‌ات را ترک نکن.
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
تو به داوود وعده فرمودی که از نسل او برتخت سلطنت خواهد نشست، و تو به وعده‌ات عمل خواهی کرد.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
و نیز به داوود گفتی که اگر فرزندانش از احکام تو اطاعت کنند، نسل اندر نسل سلطنت خواهند کرد.
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
ای خداوند، تو اورشلیم را برگزیده‌ای تا در آن ساکن شوی.
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
تو فرمودی: «تا ابد در اینجا ساکن خواهم بود، زیرا اینچنین اراده نموده‌ام.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
آذوقهٔ این شهر را برکت خواهم داد و فقیرانش را با نان سیر خواهم نمود.
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
کاهنانش را در خدمتی که می‌کنند برکت خواهم داد، و مردمش با شادی سرود خواهند خواند.
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
«در اینجا قدرت داوود را خواهم افزود و چراغ مسیح خود را روشن نگه خواهم داشت.
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
دشمنان او را با رسوایی خواهم پوشاند، اما سلطنت او شکوهمند خواهد بود.»

< Psalms 132 >