< Psalms 132 >

1 Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Cantico di Maalot RICORDATI, Signore, di Davide, E di tutte le sue afflizioni.
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
Come egli giurò al Signore, [E] fece voto al Possente di Giacobbe, [dicendo: ]
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
Se io entro nel tabernacolo della mia casa, Se salgo sopra la lettiera del mio letto;
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
Se do alcun sonno agli occhi miei, [O] alcun sonnecchiare alle mie palpebre;
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
Infino a tanto che io abbia trovato un luogo al Signore, Degli abitacoli al Possente di Giacobbe.
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
Ecco, noi abbiamo udito [che l'Arca era stata] nella [contrada] Efratea; [Poi] la trovammo ne' campi di Iaar.
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
Entriamo negli abitacoli del Signore; Adoriamo allo scannello de' suoi piedi.
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
Levati, Signore; Tu, e l'Arca della tua forza, [per entrar] nel tuo riposo.
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
I tuoi sacerdoti sieno rivestiti di giustizia, E giubilino i tuoi santi.
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
Per amor di Davide, tuo servitore, Non negare al tuo unto la sua richiesta.
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
Il Signore giurò verità a Davide, E non [la] rivocherà, [dicendo]: Io metterò sopra il tuo trono del frutto del tuo ventre.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
Se i tuoi figliuoli osservano il mio patto, E la mia testimonianza, che io insegnerò loro; [Essi], e i lor figliuoli in perpetuo, Sederanno sopra il tuo trono.
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
Perciocchè il Signore ha eletta Sion; Egli l'ha gradita per sua stanza, dicendo:
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
Questo [è] il mio riposo in perpetuo, Qui abiterò; perciocchè [questo è il luogo che] io ho desiderato.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
Io benedirò largamente la sua vittuaglia; Io sazierò di pane i suoi poveri.
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
E vestirò i suoi sacerdoti [di vesti] di liberazione; E i suoi santi giubileranno in gran letizia.
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
Quivi farò germogliare un corno a Davide; E terrò accesa una lampana al mio unto.
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
Io vestirò i suoi nemici di vergogna; E la sua benda reale fiorirà sopra lui.

< Psalms 132 >