< Psalms 132 >

1 Orin fún ìgòkè. Olúwa, rántí Dafidi nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Cantique des degrés. Éternel, souviens-toi de David, De toutes ses peines!
2 Ẹni tí ó ti búra fún Olúwa, tí ó sì ṣe ìlérí fún alágbára Jakọbu pé.
Il jura à l’Éternel, Il fit ce vœu au puissant de Jacob:
3 Nítòótọ́, èmi kì yóò wọ inú àgọ́ ilé mi lọ, bẹ́ẹ̀ èmi kì yóò gun orí àkéte mi.
Je n’entrerai pas dans la tente où j’habite, Je ne monterai pas sur le lit où je repose,
4 Èmi kì yóò fi oorun fún ojú mi, tàbí òògbé fún ìpéǹpéjú mi,
Je ne donnerai ni sommeil à mes yeux, Ni assoupissement à mes paupières,
5 títí èmi ó fi rí ibi fún Olúwa, ibùjókòó fún alágbára Jakọbu.
Jusqu’à ce que j’aie trouvé un lieu pour l’Éternel, Une demeure pour le puissant de Jacob.
6 Kíyèsi i, àwa gbúròó rẹ̀ ni Efrata: àwa rí i nínú oko ẹgàn náà.
Voici, nous en entendîmes parler à Éphrata, Nous la trouvâmes dans les champs de Jaar…
7 Àwa ó lọ sínú àgọ́ rẹ̀: àwa ó máa sìn níbi àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀
Allons à sa demeure, Prosternons-nous devant son marchepied!…
8 Olúwa, dìde sí ibi ìsinmi rẹ: ìwọ, àti àpótí agbára rẹ.
Lève-toi, Éternel, viens à ton lieu de repos, Toi et l’arche de ta majesté!
9 Kí a fi òdodo wọ àwọn àlùfáà rẹ: kí àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ kí ó máa hó fún ayọ̀.
Que tes sacrificateurs soient revêtus de justice, Et que tes fidèles poussent des cris de joie!
10 Nítorí tí Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀, má ṣe yí ojú ẹni òróró rẹ padà.
A cause de David, ton serviteur, Ne repousse pas ton oint!
11 Olúwa ti búra nítòótọ́ fún Dafidi, Òun kì yóò yípadà kúrò nínú rẹ̀, nínú irú-ọmọ inú rẹ ni èmi ó gbé kalẹ̀ sí orí ìtẹ́ rẹ.
L’Éternel a juré la vérité à David, Il n’en reviendra pas; Je mettrai sur ton trône un fruit de tes entrailles.
12 Bí àwọn ọmọ rẹ̀ yóò bá pa májẹ̀mú mi mọ́ àti ẹ̀rí mi tí èmi yóò kọ́ wọn, àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú yóò jókòó lórí ìtẹ́ rẹ láéláé.
Si tes fils observent mon alliance Et mes préceptes que je leur enseigne, Leurs fils aussi pour toujours Seront assis sur ton trône.
13 Nítorí tí Olúwa ti yan Sioni: ó ti fẹ́ ẹ fún ibùjókòó rẹ̀.
Oui, l’Éternel a choisi Sion, Il l’a désirée pour sa demeure:
14 Èyí ni ibi ìsinmi mi láéláé: níhìn-ín ni èmi yóò máa gbé: nítorí tí mo fẹ́ ẹ.
C’est mon lieu de repos à toujours; J’y habiterai, car je l’ai désirée.
15 Èmi yóò bùkún oúnjẹ rẹ̀ púpọ̀púpọ̀: èmi yóò fi oúnjẹ tẹ́ àwọn tálákà rẹ̀ lọ́rùn.
Je bénirai sa nourriture, Je rassasierai de pain ses indigents;
16 Èmi yóò sì fi ìgbàlà wọ àwọn àlùfáà rẹ̀: àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ yóò máa hó fún ayọ̀.
Je revêtirai de salut ses sacrificateurs, Et ses fidèles pousseront des cris de joie.
17 Níbẹ̀ ni èmi yóò gbé mú ìwo Dafidi yọ̀, èmi ti ṣe ìlànà fìtílà kan fún ẹni òróró mi.
Là j’élèverai la puissance de David, Je préparerai une lampe à mon oint,
18 Àwọn ọ̀tá rẹ̀ ni èmi yóò fi ìtìjú wọ̀: ṣùgbọ́n lára òun tìkára rẹ̀ ni adé yóò máa gbilẹ̀.
Je revêtirai de honte ses ennemis, Et sur lui brillera sa couronne.

< Psalms 132 >