< Psalms 129 >
1 Orin fún ìgòkè. “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá,” jẹ́ kí Israẹli kí ó wí nísinsin yìí;
En Jérusalem. Souvent ils m'ont attaqué dès ma jeunesse; que maintenant Israël dise:
2 “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá; síbẹ̀ wọn kò tí ì borí mi.
Souvent ils m'ont attaqué dès ma jeunesse, et ils n'ont rien pu sur moi.
3 Àwọn awalẹ̀ walẹ̀ sí ẹ̀yìn mi: wọ́n sì la aporo wọn gígùn.
Les pécheurs ont frappé sur mon dos; ils ont prolongé leur iniquité.
4 Olódodo ni Olúwa: ó ti ké okùn àwọn ènìyàn búburú kúrò.”
Le Seigneur en sa justice a brisé le cou des pécheurs.
5 Kí gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni kí ó dààmú, kí wọn kí ó sì yí ẹ̀yìn padà.
Qu'ils soient confondus et mis en fuite, tous ceux qui haïssent Sion.
6 Kí wọn kí ó dàbí koríko orí ilẹ̀ tí ó gbẹ dànù kí ó tó dàgbàsókè,
Qu'ils deviennent comme l'herbe des toits, qui sèche avant d'être arrachée,
7 èyí tí olóko pípa kó kún ọwọ́ rẹ̀: bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń di ìtí, kó kún apá rẹ̀.
Et qui ne remplit ni la main du faucheur ni le sein du botteleur.
8 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń kọjá lọ kò wí pé, ìbùkún Olúwa kí ó pẹ̀lú yín: àwa ń súre fún yin ní orúkọ Olúwa.
Sur eux les passants n'ont point dit: Que la bénédiction du Seigneur soit avec tous; nous vous bénissons au nom du Seigneur.