< Psalms 127 >

1 Orin fún ìgòkè. Ti Solomoni. Bí kò ṣe pé Olúwa bá kọ́ ilé náà àwọn tí ń kọ́ ọ ń ṣiṣẹ́ lásán ni; bí kò ṣe pé Olúwa bá pa ìlú mọ́, olùṣọ́ jí lásán.
A Song of Ascents. By Solomon. Unless the LORD builds the house, they who build it labour in vain. Unless the LORD watches over the city, the watchman guards it in vain.
2 Asán ni fún ẹ̀yin ti ẹ dìde ní kùtùkùtù láti pẹ́ dùbúlẹ̀, láti jẹ oúnjẹ làálàá; bẹ́ẹ̀ ni ó ń fi ìre fún olùfẹ́ rẹ̀ lójú ọ̀run.
It is vain for you to rise up early, to stay up late, eating the bread of toil, for he gives sleep to his loved ones.
3 Kíyèsi i, àwọn ọmọ ni ìní Olúwa: ọmọ inú sì ni èrè rẹ̀.
Behold, children are a heritage of the LORD. The fruit of the womb is his reward.
4 Bí ọfà ti rí ní ọwọ́ alágbára, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ èwe.
As arrows in the hand of a mighty man, so are the children of youth.
5 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí apó rẹ̀ kún fún wọn; ojú kì yóò tì wọ́n, ṣùgbọ́n wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá ní ẹnu-ọ̀nà.
Happy is the man who has his quiver full of them. They won’t be disappointed when they speak with their enemies in the gate.

< Psalms 127 >