< Psalms 127 >

1 Orin fún ìgòkè. Ti Solomoni. Bí kò ṣe pé Olúwa bá kọ́ ilé náà àwọn tí ń kọ́ ọ ń ṣiṣẹ́ lásán ni; bí kò ṣe pé Olúwa bá pa ìlú mọ́, olùṣọ́ jí lásán.
Except the LORD build the house, they labor in vain that build it: except the LORD keep the city, the watchman wakes but in vain.
2 Asán ni fún ẹ̀yin ti ẹ dìde ní kùtùkùtù láti pẹ́ dùbúlẹ̀, láti jẹ oúnjẹ làálàá; bẹ́ẹ̀ ni ó ń fi ìre fún olùfẹ́ rẹ̀ lójú ọ̀run.
It is vain for you to rise up early, to sit up late, to eat the bread of sorrows: for so he gives his beloved sleep.
3 Kíyèsi i, àwọn ọmọ ni ìní Olúwa: ọmọ inú sì ni èrè rẹ̀.
See, children are an heritage of the LORD: and the fruit of the womb is his reward.
4 Bí ọfà ti rí ní ọwọ́ alágbára, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ èwe.
As arrows are in the hand of a mighty man; so are children of the youth.
5 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí apó rẹ̀ kún fún wọn; ojú kì yóò tì wọ́n, ṣùgbọ́n wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá ní ẹnu-ọ̀nà.
Happy is the man that has his quiver full of them: they shall not be ashamed, but they shall speak with the enemies in the gate.

< Psalms 127 >