< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
Waƙar haurawa. Sa’ad da Ubangiji ya dawo da kamammu zuwa Sihiyona, mun kasance kamar mutanen da suka yi mafarki.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Bakunanmu sun cika da dariya, harsunanmu da waƙoƙin farin ciki. Sai ana faɗi a cikin al’ummai, “Ubangiji ya aikata manyan abubuwa dominsu.”
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Ubangiji ya aikata manyan abubuwa dominmu, mun kuwa cika da farin ciki.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Ka maido da wadatarmu, ya Ubangiji kamar rafuffuka a Negeb.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
Waɗanda suka yi shuka da hawaye za su yi girbi da waƙoƙin farin ciki.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Shi da ya fita yana kuka, riƙe da iri don shuki, zai dawo da waƙoƙin farin ciki, ɗauke da dammuna.

< Psalms 126 >