< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
Ein Wallfahrtslied. Als der HERR die Gefangenen Zions zurückbrachte, da waren wir wie Träumende.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Da war unser Mund voll Lachens und unsre Zunge voll Jubel; da sagte man unter den Heiden: «Der HERR hat Großes an ihnen getan!»
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Der HERR hat Großes an uns getan, wir sind fröhlich geworden.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
HERR, bringe unsre Gefangenen zurück wie Bäche im Mittagsland!
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
Die mit Tränen säen, werden mit Freuden ernten.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Wer weinend dahingeht und den auszustreuenden Samen trägt, wird mit Freuden kommen und seine Garben bringen.

< Psalms 126 >