< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
When Yahweh brought [us Israeli people] back to Jerusalem (OR, enabled us Israelis to prosper again), [it was wonderful]; it seemed as though [SIM] we were dreaming.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
We were extremely happy, and we [SYN] continued shouting joyfully. Then the [other] people-groups said about us, “Yahweh has done great things for them!”
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
[And we say, “Yes], Yahweh [truly] has done great things for us, and we are [very] happy.”
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Yahweh, when it rains, water flows in the streams again [after they were dry] [SIM]. Similarly, enable our nation to become great again like it was before.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
We cried when we planted [seeds because it was hard work preparing the soil that had not been plowed for many years]; [now we want to] shout joyfully because we are gathering a [big] harvest.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Those who cried as they carried the [bags of] seeds [to the fields] will shout joyfully when they bring the crops [to their houses at harvest time].

< Psalms 126 >