< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
A Song of Ascents. When Yahweh brought back the captives of Zion, we were like them who dream:
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then, was our mouth, filled with laughter, and our tongue with a shout of triumph, —Then, said they among the nations, Yahweh, hath done great things, with these!
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Yahweh, hath done great things with us, we are full of joy!
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Bring thou back, O Yahweh, our captives, like channels in the South.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
They who are sowing with tears, with shouting, shall reap:
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
He that, doth indeed go forth, and weep, bearing seed enough to trail along, doth, surely come in, with shouting, bringing his sheaves.

< Psalms 126 >