< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
A Song of Ascents. When the LORD turned again the captivity of Zion, we were like unto them that dream.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then was our mouth filled with laughter, and our tongue with singing: then said they among the nations, The LORD hath done great things for them.
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
The LORD hath done great things for us; [whereof] we are glad.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Turn again our captivity, O LORD, as the streams in the South.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
They that sow in tears shall reap in joy.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Though he goeth on his way weeping, bearing forth the seed; he shall come again with joy, bringing his sheaves [with him].

< Psalms 126 >