< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
When Adonai brought back those who teshuvah ·completely returned· to Zion [Mountain ridge, Marking], we were like those who dream.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then our mouth was filled with laughter, and our tongue with singing. Then they said among the nations, “Adonai has done great things for them.”
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Adonai has done great things for us, and we are glad.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Restore our fortunes again, Adonai, like the streams in the Negev.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
Those who sow in tears will reap in joy.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
He who goes out weeping, carrying seed for sowing, will certainly come again with joy, carrying his sheaves.

< Psalms 126 >