< Psalms 126 >
1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
A Song of degrees. When the LORD turned again the captivity of Zion, we were like them that dream.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then was our mouth filled with laughter, and our tongue with singing: then said they among the heathen, The LORD hath done great things for them.
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
The LORD hath done great things for us; [whereof] we are glad.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Turn again our captivity, O LORD, as the streams in the south.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
They that sow in tears shall reap in joy.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
He that goeth forth and weepeth, bearing precious seed, shall doubtless come again with rejoicing, bringing his sheaves [with him].