< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
A song of ascents. When the LORD restored the captives of Zion, we were like dreamers.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then our mouths were filled with laughter, our tongues with shouts of joy. Then it was said among the nations, “The LORD has done great things for them.”
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
The LORD has done great things for us; we are filled with joy.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Restore our captives, O LORD, like streams in the Negev.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
Those who sow in tears will reap with shouts of joy.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
He who goes out weeping, bearing a trail of seed, will surely return with shouts of joy, carrying sheaves of grain.

< Psalms 126 >