< Psalms 126 >

1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
When Jehovah brought back those who returned to Zion, we were like those who dream.
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
Then our mouth was filled with laughter, and our tongue with singing. Then they said among the nations, Jehovah has done great things for them.
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Jehovah has done great things for us. We are glad.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Turn again our captivity, O Jehovah, as the streams in the South.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
Those who sow in tears shall reap in joy.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
He who goes forth and weeps, bearing seed for sowing, shall doubtless come again with joy, bringing his sheaves.

< Psalms 126 >