< Psalms 126 >
1 Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
Der Herren hjemførte Zions Folk, som vendte tilbage, da vare vi som drømmende,
2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
da blev vor Mund fyldt med Latter og vor Tunge med Frydesang, da sagde man iblandt Hedningerne: Herren har gjort store Ting imod disse.
3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
Herren har gjort store Ting imod os; vi bleve glade.
4 Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
Hjemfør, Herre! vore fangne, lig Sydlandets Strømme.
5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
De, som saa med Graad, skulle høste med Frydesang.
6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Den, som bærer Sæden, der saas, gaar sin Gang med Graad; men han skal komme med Frydesang, naar han hjembærer sine Neg.