< Psalms 124 >

1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
A no haber estado Jehová por nosotros, díga lo ahora Israel:
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
A no haber estado Jehová por nosotros, cuando se levantaron contra nosotros los hombres;
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
Vivos nos tragaran entonces: cuando se encendió su furor en nosotros:
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
Entonces las aguas inundaran sobre nosotros: el arroyo pasara sobre nuestra alma.
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
Entonces pasaran sobre nuestra alma las aguas soberbias.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Bendito Jehová que no nos dio por presa a sus dientes.
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
Nuestra alma, como ave, escapó del lazo de los cazadores: el lazo se quebró, y nosotros escapamos.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Nuestro socorro fue en el nombre de Jehová, que hizo el cielo y la tierra.

< Psalms 124 >