< Psalms 124 >
1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
Um Canto de Ascensões. Por David. Se não tivesse sido Yahweh que estava do nosso lado, que Israel diga agora,
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
se não tivesse sido Yahweh que estava do nosso lado, quando os homens se levantaram contra nós,
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
então eles nos teriam engolido vivos, quando a ira deles foi acesa contra nós,
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
então as águas ter-nos-iam dominado, o riacho teria passado por cima de nossa alma.
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
Então as águas orgulhosas teriam passado por cima de nossa alma.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Bendito seja Yahweh, que não nos deu como presa para seus dentes.
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
Nossa alma escapou como um pássaro da armadilha do passarinho. A armadilha está quebrada, e nós escapamos.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Nossa ajuda está em nome de Yahweh, que fizeram o céu e a terra.