< Psalms 124 >
1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
Cantique des degrés.
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
Si le Seigneur n’eût été au milieu de nous, Lorsque les hommes s’insurgeaient contre nous,
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
Peut-être nous auraient-ils dévorés tout vivants: Lorsque leur fureur s’irritait contre nous,
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
Peut-être que l’eau nous aurait engloutis.
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
Notre âme a traversé un torrent: peut-être notre âme aurait passé dans une eau sans fond.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Béni le Seigneur, qui ne nous a pas donnés en proie à leurs dents.
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
Notre âme, comme un passereau, a été arrachée du filet des chasseurs: le filet a été rompu, et nous, nous avons été délivrés.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Notre secours est dans le nom du Seigneur qui a fait le ciel et la terre.