< Psalms 124 >
1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
If it had not been Adonai who was on our side, let Israel [God prevails] now say,
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
if it had not been Adonai who was on our side, when men rose up against us;
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
then they would have swallowed us up alive, when their wrath was kindled against us;
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
then the waters would have overwhelmed us, the stream would have gone over our soul;
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
then the proud waters would have gone over our soul.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Blessed be Adonai, who has not given us as a prey to their teeth.
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
Our soul has escaped like a bird out of the fowler’s snare. The snare is broken, and we have escaped.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Our help is in Adonai’s name, who made heaven and earth.