< Psalms 124 >

1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
“A psalm of the steps, or the goings up. By David.” If the LORD had not been for us, Now may Israel say,
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
If the LORD had not been for us, When men rose up against us,
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
Then had they swallowed us up alive, When their wrath burned against us;
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
Then the waters had overwhelmed us; The stream had gone over our soul;
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
The proud waters had gone over our soul.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Blessed be the LORD, Who hath not given us a prey to their teeth!
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
We have escaped like a bird from the snare of the fowler; The snare is broken, and we have escaped.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Our help is in the name of the LORD, Who made heaven and earth.

< Psalms 124 >