< Psalms 124 >
1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. “Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,” kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;
A SONG OF THE ASCENTS. BY DAVID. If YHWH had not been for us (Pray, let Israel say),
2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa, nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,
If YHWH had not been for us, In the rising up of man against us,
3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,
Then they had swallowed us alive, In the burning of their anger against us,
4 nígbà náà ni omi wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,
Then the waters had overflowed us, The stream passed over our soul,
5 nígbà náà ni agbéraga omi ìbá borí ọkàn wa.
Then proud waters had passed over our soul.
6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.
Blessed [is] YHWH who has not given us, [As] prey to their teeth.
7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ; okùn já àwa sì yọ.
Our soul has escaped as a bird from a snare of fowlers, The snare was broken, and we have escaped.
8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa, tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Our help [is] in the Name of YHWH, Maker of the heavens and earth!