< Psalms 122 >

1 Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi. Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé, “Ẹ jẹ́ kí á lọ sílé Olúwa.”
Ein Stufenlied. Von David. Ich freute mich, als sie zu mir sagten: Lasset uns zum Hause Jehovas gehen!
2 Ẹsẹ̀ wa yóò dúró ní ẹnu ibodè rẹ, ìwọ Jerusalẹmu.
Unsere Füße werden in deinen Toren stehen, Jerusalem!
3 Jerusalẹmu, ìwọ tí a kọ́ bí ìlú tí o fi ara mọ́ra pọ̀ ṣọ̀kan.
Jerusalem, die du aufgebaut bist als eine fest in sich geschlossene Stadt,
4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà máa ń gòkè lọ, àwọn ẹ̀yà Olúwa, ẹ̀rí fún Israẹli, láti máa dúpẹ́ fún orúkọ Olúwa.
wohin die Stämme hinaufziehen, die Stämme Jahs, ein Zeugnis für Israel, zu preisen den Namen Jehovas!
5 Nítorí ibẹ̀ ni a gbé ìtẹ́ ìdájọ́ kalẹ̀, àwọn ìtẹ́ ilé Dafidi.
Denn daselbst stehen die Throne zum Gericht, die Throne des Hauses Davids.
6 Gbàdúrà fún àlàáfíà Jerusalẹmu; àwọn tí ó fẹ́ ọ yóò ṣe rere.
Bittet um die Wohlfahrt Jerusalems! Es gehe wohl denen, die dich lieben!
7 Kí àlàáfíà kí ó wà nínú odi rẹ̀, àti ìre nínú ààfin rẹ̀.
Wohlfahrt sei in deinen Festungswerken, sichere Ruhe in deinen Palästen!
8 Nítorí àwọn ọkùnrin àti àwọn ẹgbẹ́ mi èmi yóò wí nísinsin yìí pé, kí àlàáfíà kí ó wà nínú rẹ̀.
Um meiner Brüder und meiner Genossen willen will ich sagen: Wohlfahrt sei in dir!
9 Nítorí ilé Olúwa Ọlọ́run wa, èmi yóò máa wá ìre rẹ̀.
Um des Hauses Jehovas, unseres Gottes, willen will ich dein Bestes suchen.

< Psalms 122 >