< Psalms 121 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì— níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?
Mis ojos se elevan a las colinas: ¿de dónde vendrá mi ayuda?
2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá, ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Tu ayuda viene del Señor, que hizo los cielos y la tierra.
3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀; ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
Que no deja que resbale tu pie; no tiene necesidad de dormir el que te guarda.
4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́, kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
Mira, los ojos del guardián de Israel no se cerrarán en el sueño.
5 Olúwa ni olùpamọ́ rẹ; Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
El Señor es tu guardián; el Señor es tu sombra en tu mano derecha.
6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
No te tocará el sol en el día ni la luna en la noche.
7 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo yóò pa ọkàn rẹ mọ́
El Señor te mantendrá a salvo de todo mal; Él cuidará tu alma.
8 Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́ láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
El Señor cuidará de tu salida y de tu entrada, desde este momento y para siempre.

< Psalms 121 >