< Psalms 121 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì— níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?
A Song of Ascents. I will lift up mine eyes, unto the mountains, From whence cometh my help!
2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá, ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
My help, is from Yahweh, who made heavens and earth.
3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀; ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
May he not suffer thy foot, to slip, May thy keeper, not slumber!
4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́, kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
Lo! neither will slumber nor sleep, The keeper of Israel.
5 Olúwa ni olùpamọ́ rẹ; Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Yahweh, is thy keeper, Yahweh, is thy shade, on thy right hand:
6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
By day, the sun, shall not smite, nor, the moon, by night.
7 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo yóò pa ọkàn rẹ mọ́
Yahweh, will keep thee from all harm, He will keep thy life.
8 Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́ láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
Yahweh, will keep thy going out and thy coming in, from henceforth, even unto times age-abiding.

< Psalms 121 >