< Psalms 121 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì— níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?
A Song of Ascents. I will lift up my eyes to the hills. Where does my help come from?
2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá, ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
My help comes from the LORD, who made heaven and earth.
3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀; ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
He will not allow your foot to be moved. He who keeps you will not slumber.
4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́, kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
Behold, he who keeps Israel will neither slumber nor sleep.
5 Olúwa ni olùpamọ́ rẹ; Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
The LORD is your keeper. The LORD is your shade on your right hand.
6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
The sun will not harm you by day, nor the moon by night.
7 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo yóò pa ọkàn rẹ mọ́
The LORD will keep you from all evil. He will keep your soul.
8 Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́ láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
The LORD will keep your going out and your coming in, from this time forward, and forever more.

< Psalms 121 >