< Psalms 121 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì— níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?
Píseň stupňů. Pozdvihuji očí svých k horám, odkudž by mi přišla pomoc.
2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá, ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Pomoc má jest od Hospodina, kterýž učinil nebe i zemi.
3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀; ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.
Nedopustíť, aby se pohnouti měla noha tvá, nedřímeť strážný tvůj.
4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́, kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.
Aj, nedřímeť, ovšem nespí ten, kterýž ostříhá Izraele.
5 Olúwa ni olùpamọ́ rẹ; Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Hospodin strážce tvůj, Hospodin zastínění tvé tobě po pravici.
6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.
Nebudeť bíti na tě slunce ve dne, ani měsíc v noci.
7 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo yóò pa ọkàn rẹ mọ́
Hospodin tě ostříhati bude ode všeho zlého, ostříhati bude duše tvé.
8 Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́ láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.
Hospodin ostříhati tě bude, když vycházeti i vcházeti budeš, od tohoto času až na věky.

< Psalms 121 >