< Psalms 120 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
Cantique des pèlerinages. J'ai invoqué l'Éternel dans ma détresse, Et il m'a exaucé.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
Éternel, délivre mon âme des lèvres menteuses, De la langue perfide!
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
Quelle sera ta rétribution, Quel sera ton profit, langue perfide?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
— Les flèches aiguës du guerrier, Avec les charbons ardents du genêt! —
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Malheureux que je suis, de séjourner dans Mésec, De demeurer sous les tentes de Kédar!
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
Trop longtemps mon âme a demeuré Parmi ceux qui haïssent la paix.
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
Je veux la paix; mais, dès que j'ouvre la bouche, Ils veulent la guerre!

< Psalms 120 >