< Psalms 120 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
A song of ascents. In my distress I called out to Yahweh, and he answered me.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
Rescue my life, Yahweh, from those who lie with their lips and deceive with their tongues.
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
How will he punish you, and what more will he do to you, you who have a lying tongue?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
He will punish you with the arrows of a warrior sharpened over burning coals of the broom tree.
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Woe is me because I temporarily live in Meshech; I lived previously among the tents of Kedar.
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
For too long I have lived with those who hate peace.
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
I am for peace, but when I speak, they are for war.

< Psalms 120 >