< Psalms 120 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
A Song of Ascents. Unto Yahweh, in the distress that befell me, I cried—and he answered me.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
O Yahweh! rescue thou my soul—from the false lip, from the deceitful tongue.
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
What shall be given to thee, and what shall be added to thee, thou deceitful tongue?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
The arrows of the hero sharpened, with burning coals of broom.
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Woe is me, That I sojourn in Meshek, —That I abide near the tents of Kedar!
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
Long, hath my soul had her dwelling with him that hateth peace:
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
I, am for peace, and verily I speak, They, are for war!

< Psalms 120 >