< Psalms 120 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
A song of ascents. In distress I cried to the Lord, and he answered me.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
“Deliver me, Lord, from the lip that is false and the tongue that is crafty.”
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
What shall he give to you, you tongue that is crafty? What yet shall he give to you?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
Arrows of warrior, sharpened, with glowing broom coals together.
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Woe is me that I sojourn in Meshech, that I live by the tents of Kedar.
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
Already too long have I dwelt among those who hate peace.
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
I am for peace: but when I speak of it, they are for war.

< Psalms 120 >