< Psalms 120 >
1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
A Song of Degrees. In mine affliction I cried to the Lord, and he listened to me.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
Deliver my soul, O Lord, from unjust lips, and from a deceitful tongue.
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
What should be given to you, and what should be added to you, for [your] crafty tongue?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
Sharpened weapons of the mighty, with coals of the desert.
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Woe is me, that my sojourning is prolonged; I have tabernacled amongst the tents of Kedar.
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
My soul has long been a sojourner;
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
I was peaceful amongst them that hated peace; when I spoke to them, they warred against me without a cause.