< Psalms 120 >

1 Orin fún ìgòkè. Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi, ó sì dá mi lóhùn.
A Song of Ascents. In my distress, I cried to the LORD. He answered me.
2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.
Deliver my soul, LORD, from lying lips, from a deceitful tongue.
3 Kí ni kí a fi fún ọ? Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?
What will be given to you, and what will be done more to you, you deceitful tongue?
4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun, pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.
Sharp arrows of the mighty, with coals of juniper.
5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki, nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!
Woe is me, that I live in Meshech, that I dwell among the tents of Kedar!
6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.
My soul has had her dwelling too long with him who hates peace.
7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí; ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.
I am for peace, but when I speak, they are for war.

< Psalms 120 >