< Psalms 12 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Neghmichilerning béshigha tapshurulup, shéminit bilen oqulsun dep, Dawut yazghan küy: — Qutquzghaysen, Perwerdigar, chünki ixlasmen adem tügep ketti; Ademler arisidin sadiq möminler ghayip boldi.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
Herbirsi öz yéqinlirigha yalghan éytidu; Xushametchi lewlerde, aliköngüllük bilen sözlishidu.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Perwerdigar barliq xushametchi lewlerni, Hakawurlarche sözleydighan tilni késiwetkey!
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
Ular: «Tilimiz bilen ghelibe qilimiz; Lewlirimiz bolsa özimizningkidur; Kim bizge Reb bolalisun?» — deydu.
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
«Ézilgüchi ajizlarni basqan zulum wejidin, Miskinlerning ahuzarliri wejidin, Hazirla ornumdin turay» — deydu Perwerdigar, «Men ulargha, ular zariqip kütken azadliqni yetküzimen».
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Perwerdigarning sözliri bolsa sap sözlerdur; Ular yette qétim saplashturulghan, Sapal qazanda tawlan’ghan kümüshtektur.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Sen Perwerdigar, ularni saqlaysen; Sen [möminlerni] mushu dewrdin menggüge qoghdaysen;
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
[Chünki] rezil ademler heryanda ghadiyip yürüshidu, Peskeshlik insan baliliri arisida aliyjanabliq dep maxtalmaqta!