< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Para o Músico Chefe; sobre uma lira de oito cordas. Um Salmo de David. Help, Yahweh; pois o homem piedoso cessa. Pois os fiéis falham entre os filhos dos homens.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
Todos mentem ao seu próximo. Eles falam com lábios lisonjeiros, e com um coração duplo.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Que Yahweh corte todos os lábios lisonjeiros, e a língua que se vangloria,
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
que disseram: “Com nossa língua prevaleceremos”. Nossos lábios são os nossos próprios. Quem é o senhor sobre nós”?
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
“Por causa da opressão dos fracos e por causa do gemido dos necessitados, Agora eu me levantarei”, diz Yahweh; “Vou colocá-lo em segurança contra aqueles que o malignizam”.
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
As palavras de Yahweh são palavras impecáveis, como prata refinada em um forno de barro, purificada sete vezes.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Você vai mantê-los, Yahweh. Você os preservará desta geração para sempre.
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Os malvados caminham de todos os lados, quando o que é vil é exaltado entre os filhos dos homens.

< Psalms 12 >