< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Au maître-chantre. — Pour voix de basse. — Psaume de David. Sauve-nous, ô Éternel! Car les hommes pieux disparaissent; Il n'y a plus de fidèles parmi les fils des hommes.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
Ils s'adressent l'un à l'autre des paroles mensongères; Ils parlent avec des lèvres flatteuses, Avec un coeur double.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Que l'Éternel détruise toutes les lèvres flatteuses, La langue qui parle avec orgueil,
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
Et tous ceux qui disent: «Notre langue nous assure la victoire; Nos lèvres sont notre force: Qui serait notre maître?»
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
A cause de l'oppression des malheureux Et du gémissement des pauvres, Maintenant, dit l'Éternel, je me lèverai; Je leur donnerai le salut après lequel ils soupirent!
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Les paroles de l'Éternel sont des paroles pures; C'est un argent affiné au creuset, dans l'argile, Et qui est épuré par sept fois.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Toi, ô Éternel, tu garderas les justes; Tu nous défendras contre cette génération, à perpétuité!
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Les méchants s'agitent de toutes parts, Quand la bassesse règne parmi les fils des hommes.

< Psalms 12 >