< Psalms 12 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Jusqu'à la Fin, psaume de David, en octave. Sauve-moi, Seigneur, parce que la sainteté a défailli, et que les vérités ont été amoindries par les fils des hommes.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
Chacun a dit à son prochain des choses vaines; leurs lèvres sont menteuses, et ils ont parlé avec un cœur double.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Que le Seigneur perde les lèvres menteuses et les langues pleines de jactance,
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
Qui ont dit: Nous ferons valoir la puissance de notre langue; nos lèvres dépendent de nous; qui est notre maître?
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
Je me lèverai maintenant, dit le Seigneur, à cause de la misère des indigents et du gémissement du pauvre; je le mettrai en sûreté, et avec lui j'agirai en toute liberté.
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Les paroles de Dieu sont des paroles saintes, de l'argent éprouvé par le feu, dégagé de la terre, purifié sept fois.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Toi, Seigneur, tu nous conserveras, tu nous garderas de cette génération à jamais!
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Les impies se promènent dans un cercle; c'est en vue de ta grandeur que tu as multiplié les fils des hommes.